Sunday, January 17, 2016

Nigba kan ni Betlehemu

Nigba kan ni Betlehemu
Ile kekere kan wa
Nib'i'ya kan te mo're si
Lori ibuje eran
Maria n'iya omo na
Jesu Kristi l'omo na

O t'orun wa s'ode aye
On l'Olorun Oluwa
O f'ile eran se ile
'Buje eran fun 'busun
Lodo awon otosi
Ni Jesu gbe li aye

Ni gbogbo igba ewe Re
O ngboran o si mb'ola
O feran Osi nteriba
Fun iya ti ntoju Re!
Oye ki gbogbo' omode
K'o se olugboran be

'Tori on je awose wa
A ma dagba bi awa
O kere ko le da nkan se
A ma sokun bi awa
O si le ba wa daro
O le ba wa yo pelu

A o foju wa ri nikehin
Ni agbara ife re
Nitori omo rere yi
Ni Oluwa wa l'orun
O nto awa omo re
S'ona ibiti On lo

Ki se ni ibuje eran
Nibiti malu njeun
L'awa o ri; sugbon lorun
Lowo otun 'Olorun
'Gba 'won 'mo Re b'irawo
Ba wa n'nu aso la




Once in royal Davids city,
Stood a lowly cattle shed,
Where a mother laid her Baby,
In a manger for His bed:
Mary was that mother mild,
Jesus Christ, her little Child.

He came down to earth from heaven,
Who is God and Lord of all,
And His shelter was a stable,
And His cradle was a stall:
With the poor, and mean, and lowly,
Lived on earth our Saviour holy.

For He is our childhood's pattern;
Day by day, like us, He grew;
He was little, weak, and helpless,
Tears and smiles, like us He knew;
And He cares when we are sad,
And he shares when we are glad.

And our eyes at last shall see Him,
Through His own redeeming love;
For that Child so dear and gentle,
Is our Lord in heaven above:
And He leads His children on,
To the place where He is gone.








No comments:

Post a Comment